Ohun tí ó bá wu ènìyàn ni ó lè fi ìgbé-ayé rẹ̀ ṣe o! ṣùgbọ́n, ẹni a wí fún, ọba jẹ́ ó gbọ́!

Ìròyìn tí a rí lórí ẹ̀rọ ayélujára X, sọ pé ẹnikan tí orúkọ rẹ̀ njẹ́ Gbóyèga Isiaka, tí wọ́n sọ pé ó nṣojú “Àríwá Yewa àti Imeko-Afon“, Ìpínlẹ̀ Ògùn tí ó jẹ́ ara Democratic Republic of the Yoruba (D.R.Y), wọ́n ní ó nṣe ojú wọn ní ilé-ìgbìmọ̀ aṣojú-ṣ’òfin ní ìlú Nàìjíríà, ni ó sọ ọ̀rọ̀ kan síta o.

Àkọ́kọ́ ná, ìpínlẹ̀ Ògùn jẹ́ ìkan nínú àwọn ìpínlẹ̀ Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá (D.R.Y), èyí tí ó sì ti jáde kúrò lára Nàìjíríà láti ogúnjọ́ oṣù bélú ẹgbàá-ọdún ó lé méjìlélógún, bẹ́ẹ̀ náà ni a ti ṣe Ìpolongo Ìṣèjọba-Ara-Ẹni wa láti ọjọ́ kéjìlá oṣù igbe ẹgbàá-ọdún ó lé mẹ́rinlélógún tí a wà nínú rẹ̀ yí: nítorí náà,

kò yé wa o, kíni ìtumọ̀ pé ẹnikan nṣojú Yewa, orílẹ̀-èdè D.R.Y, ní ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin Nàìjíríà, tí ó yàtọ̀ pátápátá sí D.R.Y! Kí ló njẹ́ bẹ́ẹ̀!? Ààà, ìwọ Gbóyèga Isiaka yẹn, o tí dá ọ̀ràn o! O ti ṣe àkọlù sí Ìṣèjọba-Ara-Ẹni Orílẹ̀-Èdè D.R.Y.

Kí wá ni ọ̀daràn Gbóyèga Isiaka náà sọ o? Ìròyìn náà sọ pé ó nsọ̀rọ̀ nípa ètò ẹ̀yáwó fún àwọn akẹ́kọ ilé-ẹ̀kọ́ gígá gbogbonìṣe ní ìlú nàìjíríà.

Ẹ jọ̀wọ́, ojúlówó ọmọ Ìbílẹ̀ Yorùbá (Indigenous Yoruba People, I.Y.P) ti Democratic Republic of the Yoruba (D.R.Y), ẹ máṣe yá owó kankan tàbí gba ohunkóhun lọ́wọ́ Nàìjíríà o!

Àkọ́kọ́, ẹ kìí ṣe ọmọ Nàìjíríà. Èkéjì, tí ẹ bá gba owó tí Nàìjíríà nfún àwọn ọmọ Nàìjíríà, ẹ ti sọ pé ẹ kìí ṣe ọmọ D.R.Y nìyẹn o! Àrọ́mọ-d’ọmọ yín, láyé, kò sì lè ní ẹ̀tọ́ sí ohunkóhun tó wà fún ọmọ ìbílẹ̀ Yorùbá.

The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.