@newscentral (a lo fọ́nrán yí fún ẹ̀kọ́ nìkan, a sì ṣe ìdánimọ̀ fún àwọn tí ó ní ẹ̀tọ́ lórí rẹ̀.)

Ọ̀rọ̀ yìí dá lórí bí onímọ̀ ìṣègùn òyìnbó, Dókítà Phillip Njemanze ti ṣe àtúpalẹ̀ ìgbésẹ Bill Gates lórí bí ó ti fẹ́ gba ọ̀nà ètò ìlera láti dín àwọn ènìyàn kù. Àwọn kókó tí dókítà náà f’ẹnu bà nìwọ̀nyí:

Ní àkọ́kọ́, wọ́n tí gbé owó gidi fún àwọn aṣòfin ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ilu agbésùnmọ̀mí Nàìjíríà, àwọn alájẹbánu àti apanijayé, tí kò ní ìfẹ́ ọmọ ènìyàn. Àwọn tó yẹ kó dáàbò bo àwọn ara ìlú náà ló gba òbítíbitì owó láti ṣe òfin pé oníṣèègùn òyìnbó ní agbára láti yọ ẹ̀yà ara aláìsàn láì sọ fun tàbí láì gba àṣẹ lọ́wọ́ rẹ̀.

Lẹ́ẹ̀kejì ẹ̀wẹ̀, awon ìmùlẹ̀ ìwà búburú yìí ni àgbáyé, tí wọ́n jẹ́ alájọṣiṣẹ́pọ̀ pẹ̀lú Bill Gates nípa yíyọ ẹ̀yà ara ènìyàn tí ra gbogbo ilé ìwòsàn ìjọba tí ìlú agbésùnmọ̀mí apanilẹ́kún jayé Nàìjíríà láti lò fún iṣẹ́ ibi yìí.

Ìgbésẹ kẹta ni pé Bill Gates ti gbé owó gidi kalẹ̀ láti kọ́ ilé ìwòsàn ìgbàlódé káàkirì ìlú búburú Nàìjíríà, kí ó lè rọrùn fún wọn láti ṣiṣẹ́ ibi náà, wọn lè wá fi ìpolongo gbe lárugẹ bí ilé ìwòsàn tí ó dára jùlọ ni, kí gbogboo àwọn ènìyàn lè máa rọ́ lọ sibẹ̀, ẹ̀yà ara yíó sì máa sọnù.

Ọ̀nà kẹrin tí ó tún gbà ní láti ṣe ìdúnàádúrà pẹ̀lú àwọn òṣìṣẹ́ ìlera ìlú apaniṣayọ̀ Nàìjíríà pé kí wọ́n sọ iye owó tí ó tẹ́ wọn l’ọ́run kí òun san fún wọn láti jáwọ́ nínú iṣẹ́ ìlera pátápátá. Àwọn òṣìṣẹ́ ètò ìlera bíi dókítà, àwọn apo-òògùn, àwọn tó nṣe àyẹ̀wò fínnífínní sí àgọ́ ara láti mọ irú àìsàn tó nṣe ènìyàn, ó ní kí wọ́n fi iṣẹ́ náà silẹ̀ fún àwọn àjèjì tí òun nkó bọ̀, tí á máa pa irọ́ kí wọ́n lè máa yọ ẹ̀yà ara àwọn aláìsàn.

Ó wá hàn gbangba pé ọ̀tá Ọlọrun, ọ̀tá ènìyàn pátápátá ni Bill Gates yìí tí  ó ní èrò búburú bayii, tó ńwá bó ṣe fẹ́ dín àwọn ènìyàn kù tí ó wá jẹ́ ètò ìlera tí ó yẹ kí a ni ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rè ní ó dojúkọ, tí àwọn ìjọba agbésùnmọ̀mí Naijiria náà, nítorí àjẹbánu àti àìní ìfẹ́ ara ìlú àti ìmọtaraẹni nìkan, wọ́n wá fi ọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú Bill Gates láti pa ara ìlú wọn run. Ṣugbọ́n àwa dúpẹ́ pé Ọlọ́run ti yọ àwa ọmọ Aládé kúrò nínú ìlú agbèsùnmọ̀mí naa.

Democratic republic of the Yoruba is no longer part oƒnigeria. Anyone counting the 7 states of the yoruba nation with nigeria is committing a crime. Indigenous yoruba people should be warned!
Ìròyìn Òmìnira Olojoojumọ – Bèrè fún ẹ̀da títí rẹ!

Àwa ìran ọmọ Aládé a kú oríire pé ní déédé àsìkò yí, ní déédé ìgbà yí Ọlọ́run kọjú sí wa ṣe ni oore nípa òmìnira ilẹ̀ Yorùbá kúrò nínú ìlú tí wọ́n npè ní Nàìjíríà, ìlú amúnisìn, ìlú apanilẹ́kún jayé, ìlú a sọni di kòrofo. Èyí fí hàn gbangba pé ọpẹ́lọpẹ́ Olódùmarè tí Ó rán wòlíì Rẹ̀ sí  àwa ọmọ Aládé, ẹni bí ọkàn Rẹ̀ dìde fún òmìnira wa, màmá wa Olóyè Ìyá Ààfin Modupẹọla Onitiri-Abiọla, kíni ìpín wa ìbá ti jẹ́ lónìí l’órílẹ̀ èdè apaniṣayọ̀ Nàìjíríà yìí, tí ìjọba ibẹ̀ ti gba owó ẹ̀mí gbogbo ọmọ ìlú wọn láti yọ ẹyà ará wọn. A kú oríire lẹ́ẹ̀kan si o.

Nítorínáà, ẹnikẹ́ni tó bá ní ìfẹ́ ara rẹ̀ ó yẹ kí ó fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn Adele wa ní gbogbo ọ̀nà. Ìpinnu Olódùmarè ní àwa ọmọ Aládé yíò máa múṣẹ nínú ayé wa nígbàtí àwọn ọ̀tá òmìnira yíò wà nínú ìpayín keke.

Àwa ọmọ ìbílẹ̀ Yorùbá (Indigenous Yorùbá People, I.Y.P) ẹ jẹ́ kí a ma jó, ka ma yọ̀, ká sì ma yin Ọlọ́run lógo fun ìkéde òmìnira wa tó ti ṣẹlẹ̀ ní ogúnjọ́ oṣù Bélú ẹgbẹ̀wá-ọdún-ó-lé-méjìlelogun àti ìbúra wọlé àwọn Adelé wa ní ọjọ́ Kejìlá oṣù Igbe ẹgbẹ̀wá-ọdún-ó-lé-mẹ́rìnlélógún ti olórí ìjọba Adelé wá, bàbá wa Mobọlaji Ọlawale Akinọla Ọmọkọrẹ ati àwọn Adelé yòókù sí tí nṣiṣẹ́ lọ láti ìgbà náà.

Àwọn ajẹgàba tí wọ́n ṣì nlérò pé agbára wá tí wọ́n lè lò lé wa lórí tí bẹ̀rẹ̀ síi kan àbùkù àti ẹ́tẹ́, yíò farahàn láì pẹ́. Ayọ̀ àwa I.Y.P ti dé o.

ỌLỌ́RUN OLÓDÙMARÈ, ÀWÁMÁRIDÍ, NÍSIÌYÍ, BA GBOGBO OHUN-IBI JẸ́, PÁTÁPÁTÁ; GBOGBO MÁJẸ̀MÚ ÌRÁNṢẸ́-ẸNI-IBI, ÀṢÌTÁÁNÌ, GBOGBO ÌLÉRÍ, ÈTÒ, ÈTE, ÀTI ÈRÒ TÍ Ó LÒDÌ SÍ ORÍLẸ̀-ÈDÈ YORÙBÁ, ÌRAN YORÙBÁ, ILẸ̀ YORÙBÁ, ÌṢÈJỌBA YORÙBÁ, AGBÈGBÈ-ÀJOGÚNBÁ YORÙBÁ. NÍ AGBÁRA TÍ ỌLỌ́RUN FI NJẸ́ ÈMI-NI, KÍ ÌPARUN NÁÀ ṢẸLẸ̀ SÍ ÀWỌN Ọ̀TÁ YORÙBÁ WỌ̀NYÍ, LỌ́WỌ́LỌ́WỌ́ BÁYI

OLÓDÙMARÈ, ALÁGBÁRA, TÍ Ó NÍ IPÁ; OLÓDÙMARÈ TÍ Ó NÍ IPÁ LÓJÚ OGUN, ỌLỌ́RUN ÀWỌN ỌMỌ-OGUN, ṢE ÌPARUN PÁTÁPÁTÁ, NÍSIÌYÍ, FÚN ÀṢẸ, AGBÁRA ÀTI IPÒ TÍ WỌ́N NLÒ LÁTI JẸGÀBA LÓRÍ ORÍLẸ̀-ÈDÈ OLÓMÌNIRA TIWANTIWA TI YORÙBÁ, ÌRAN YORÙBÁ, ILẸ̀ YORÙBÁ, ÌṢÈJỌBA YORÙBÁ, AGBÈGBÈ-ÀJOGÚNBÁ YORÙBÁ.

ṢE ÌPARUN FÚN GBOGBO ÌWÀ ÌDÚKOKÒ, ÌJẸGÀBA, DÍDẸ́RÙBANI, ÌHÀLẸ̀, ÌGBÓGUN-TINI, TÍ WỌ́N DOJÚKỌ ỌMỌ-ÌBÍLẸ̀-YORÙBÁ, TI ORÍLẸ̀-ÈDÈ OLÓMÌNIRA TIWANTIWA TI YORÙBÁ