Ní orílẹ̀ èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá (Democratic Republic of the Yorùbá D.R.Y), gẹ́gẹ́ bí a ti mọ́ wípé lórí òtítọ́ àti òdodo ni a gbé ìpìlẹ̀ wa lé, nítorí náà, kò ní sí ojúsàájú nínú gbogbo ohun tí a bá ń ṣe, pàápàá ní àkókò yíyan adarí tàbí aṣojú, yálà ní ilé iṣẹ́ tàbí nínú ètò ìsèjọba.

Àwa ojúlówó ọmọ Ìbílẹ̀ Yorùbá (Indigenous Yorùbá People I.Y.P) nìkan ni yóò máa wà ní ipò asíwájú ní orílẹ̀ èdè wa. Gẹ́gẹ́ bí màmá wa, ìyá ààfin Modupẹọla Onitiri-Abiọla ṣe máa ń sọ wípé, lẹ́yìn Ọlọ́run Olódùmarè, Yorùbá ni àkọ́kọ́.

Fún ìdí èyí, aò ní gba àjòjì kankan láàyè láti wà ní ipò adarí, aṣojú tàbí aṣíwájú ní orílẹ̀ èdè D.R.Y.

Bẹ́ẹ̀ sì ni kò ní sí àyè fún àgàbàgebè, gbígba owó ẹ̀yìn tàbí ojúsàájú nínú ètò ipò yíyan, ẹni tí ipò náà bá tọ́ sì tó sì ní àtìlẹ́yìn àwọn ará ìlú jùlọ ni yóò jáwé olúborí, nítorí pé bákannáà ni gbogbo wa, àparò kan kò ní ga jù’kan lọ ní ilẹ̀ Yorùbá.

The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.