The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.

Ìdàgbàsókè gbogbo ilẹ̀ Yorùbá ni ó jẹ ìjọba Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá (Democratic Republic of the Yoruba, D.R.Y) lógún, lábẹ́ ìṣàkóso Àlàkalẹ̀ tí Olódùmarè gbé fún Ìran Yorùbá, nípasẹ̀ Màmá wa, Ìyá-Ààfin Modúpẹ́ Onítirí-Abíọ́lá.

Gẹ́gẹ́bí Màmá wa ti sọ, gbogbo ilẹ̀ Yorùbá ni ó máa ní ìdàgbàsókè àti ìgbá’yé gbádùn. Èyí tó jẹ́ pé ibi yóò wù kí a wà, ojúlówó ohun amáyédẹrùn àti ìgbé-ayé àláfíà ni ó máa wà ní àrọ́wọ́to.

Láti mú èyí wá sí ìmúṣẹ, ipele mẹ́rin ni yóò wà nínú ètò ìdàgbàsókè káàkiri ilẹ̀ Yorùbá – ipele “Ìlú-Nlá” (Urban); “Ìlú Kékèké” (Sub-Urban); “Ìgbèríko” (Rural) àti “Ẹsẹ̀kùkú” (Sub-Rural). Bẹ́ẹ̀ ni ipele kọ̀ọ̀kan sì ní ojúṣe tirẹ̀ ní orílẹ̀-èdè D.R.Y.

Èyí túmọ̀ sí pé ipele tí àgbègbè kan bá wà ni ó máa ṣe àpèjúwe irú ohun amáyédẹrùn tí yóò wà níbẹ̀ yàtọ̀ sí àwọn bí omi, títì t’ó dára, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ, tí ó máa wà ní’bi gbogbo.

Gẹ́gẹ́bí àpẹrẹ, agbègbè t’ó jẹ́ pé àwọn ní wọ́n npèsè oúnjẹ fún orílẹ̀-èdè wa, ó ní àwọn ohun ìdàgbàsókè tí ó gbọ́dọ̀ wà ní’bẹ̀; agbègbè tí ó jẹ́ pé ibẹ̀ ni àwọn ilé-iṣẹ́ ẹ̀rọ gbogbonìṣe pọ̀ sí, ó ní bí a ṣe máa ṣe ètò ìdàgbàsókè ibẹ̀, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.

Nípasẹ̀ èyí, Ìgbèríko ní iṣẹ́ tirẹ̀ ní Orílẹ̀-Èdè tí ìlú-nlá kò lè ṣe: irú ìdàgbàsókè tí ó máa mú iṣẹ́ ìgbèríko dùn-ún ṣe, nínú ìrọ̀rùn, ni ó máa wà ní’bẹ̀, yàtọ̀ sí àwọn ohun amáyédẹrùn tí ó jẹ́ kòseémá nìí gbogbo D.R.Y.

Ohun tí a ń sọ ni pé Ìgbèríko ní D.R.Y kìí ṣe oko lásán tí ènìyàn máa p’ẹ̀gàn, ṣùgbọ́n yóò jẹ́ ibi àmúyangàn tí ipò rẹ̀ ní Orílẹ̀-Èdè kò ní ṣeé fi ọwọ́ rọ́ s’ẹ́yìn.