Ọmọ ìlú Agbésùnmọ̀mí Nàìjíríà kan ni a rí fídíò rẹ̀ o, tí ó nbéèrè lọ́wọ́ ìjọba wọn pé kí ó wá ṣe àlàyé, ohun tí kò yé àwọn: tórí ìjọba sọ pé ilé-iṣẹ́ ìfọ’po tí ó wà ní ìlú Warri kò ṣiṣẹ́!

Ṣùgbọ́n, ọkùnrin tó sọ̀rọ̀ náa sọ pé àwọn ṣe àkíyèsí pé t’ó bá ti di bíi aago-méjìlá òru, àwọn ọkọ̀ agbé’po máa nlọ sí ilé-iṣẹ́ ìfọ’po náà; tí ó bá sì ti wá di bí aago méjì-sí-mẹ́ta ààjìn, àwọn ọkọ̀ náà á wá jáde kúrò ní’bẹ̀!

Ó ní òun ò sọ pé ohunkóhun nṣẹlẹ̀, ṣe ni òun kàn fẹ́ kí ìjọba ó ṣe àlàyé fún àwọn o! – ilé-iṣẹ́ ìfọ’po tẹ́ẹ ní kò ṣiṣẹ́, kíni àwọn ọkọ̀ elépo lọ nṣe níbẹ̀ lójoojúmọ́, tí wọ́n á wọlé l’aárin òru ní bíi aago méjìlá, tí wọ́n sì njáde kúrò níbẹ̀ tó bá ti di aago méjì sí mẹ́ta ààjìn? Ó ní ìbéèrè l’òun béèrè o!

Àwa náa ní ká sọọ́ ni o! pé ohun tí a gbọ́ tí ọmọ ìlú akótilétà nàìjíríà kan sọ nìyẹn o! Àwa ọmọ Yorùbá ò ńkúkú ṣe ara apaná ògo nàìjíríà mọ́, Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá (Democratic Republic of the Yoruba, D.R.Y) ni wá; ilẹ̀ wa ò sí l’ara Nàìjíríà mọ́, ṣíbẹ̀ nàìjíríà nhùwà ọ̀daràn, wọn nfi ipá jẹgàba lórí ilẹ̀ wa, bíi pé wọn ò mọ̀ pé D.R.Y ti kúrò lára wọn láti ogúnjọ́ oṣù bélú ẹgbàá ọdún ó lé méjìlélógún, a sì ti bẹ̀rẹ̀ ìjọba wa láti ọjọ́ kéjìlá oṣù ìgbe, ẹgbàá-ọdún ó lé mẹ́rin-lé-l’ogún yí; jíjẹgàba tí wọn bẹ̀rẹ̀ lẹ́yìn tí a tí kúrò nínú nàìjíríà, òun ni ìròyìn náà ṣe jẹ́ èyí tí a f’ẹnu kan: apanilẹ́kún nàìjíríà, jáde kúrò lórí ilẹ̀ D.R.Y! Gbé ìwà agbésùmọ̀mí rẹ kúrò lórí ilẹ̀ wa!

The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.
Ìròyìn Òmìnira Olojoojumọ – Bèrè fún ẹ̀da títí rẹ!