Títí láé ni àwa ìran Yorùbá yóò máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Olódùmarè tó rán ẹni bí ọkàn Rẹ̀ sí wa, màmá wa ìyá ààfin Modupẹọla Onitiri-Abiọla láti gbà wa lọ́wọ́ amúnisìn àti láti dá wa padà sí orírun wa.

Gẹ́gẹ́ bí màmá wa MOA ṣe máa ń ṣọ wípé, ní orílẹ̀ èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá (Democratic Republic of the Yorùbá, D.R.Y), èdè Yorùbá ni a óò máa sọ ní ilé iṣẹ́, ilé ẹ̀kọ́ àti gbogbo ibi ní ilẹ̀ Yorùbá. 

Èyí yóò mú ẹwà èdè Yorùbá búyọ nítorí pé kò ní sí àmúlùmúlà rárá, bí a bá ṣe ń sọ̀rọ̀ ní èdè Yorùbá pẹ̀lú òwe àti àkànlò èdè, èyí yóò mú kí gbólóhùn náà lóòrìn kó sì ní ìtumọ̀ kíkún.

Láti kékeré ni a óò tí máa kọ àwọn ọmọ wa ní èdè Yorùbá, yàtọ̀ sí òfegè Yorùbá tí a ń sọ láyé òde òní. Èdè Yorùbá ni a óò fi máa kọ́ wọn ní ilé ìwé, yóò sì jẹ́ kí ẹ̀kọ́ náà yé wọn dáadáa.

Nítorí náà, a rọ gbogbo àwa ojúlówó ọmọ Ìbílẹ̀ Yorùbá (Indigenous Yorùbá People I.Y.P) láti fi ọwọ́ so’wọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn adelé wa, kí ẹwà àti ògo tí Olódùmarè fún ìran Yorùbá leè búyọ.

The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.